A bí Moshood Olalekan Adeoti ni Ilú Ìwo, ijọba ibilẹ Iwo ní ìpínlẹ̀ Osun lọjọ́ kẹ́tàdínlogun oṣù kejì ọdún 1953
Ó bẹ̀rẹ̀ ilé ìwé alákọbẹ̀rẹ̀ ní District Council Primary Schoollọdun 1959 àti Aipate Day School lọdun 1964, lẹ́yìn náà ló lọ ilé ìwé Grammer lọdun 1974
Moshood Adeoti gboyè ìmọ ìṣòwò láti Fasiti Benin lọdún 1984
Moshood Olalekan Adeoti jẹ alága ẹgbẹ́ òṣèlú Alliance For Democracy 1998-2003, alága ẹgbẹ́ òṣèlú Action Congress 2006-2010 àti alága Action Congress of Nigeria ti alaga àkọkọ fún ẹgbk oselu APC 2010-2011
Isiaka Oyetola
All Progressives Congress (APC)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
Isiaka Adegboyega ti wọn bi ni ilu Iragbiji, ni ijọba ibilẹ Boripe ni ipinlẹ Ọsun.
Ọdun 1997 ni Oyetola ti darapọ mọ sise oselu, ati wipe o pẹlu awọn to da ẹgbẹ oselu Alliance for Democracy AD silẹ ni ọdun 1998.
Biotilẹjẹpe ogun ọdun niyi ti Oyetọla ti n se oselu, igba akọkọ ni yii ti yoo ma a dije du ipo labẹ ẹgbẹ oselu kan kan.
Amọ, iroyin kan ni wipe oun ni ẹyinoju Alaga Ẹgbẹ Oselu APC, Asiwaju Ahmed Tinubu ati Gomina Ipinlẹ Osun, Rauf Aregbesola
Alhaji Fatai Akinbade
African Democratic Congress (ADC)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
O darapọ mọ ilẹeṣẹ ijọba Ipinlẹ Ọṣun nibi to ti ṣiṣẹ fun ọdun mẹrindinlogun labẹ akoso ijọba oloogun mẹta ati ijọba alagbada Olagunsoye Oyinlọla.
Wọn yan Akinbade gẹgẹ bii akọwe ijọba Ipinlẹ Ọṣun nigba iṣakosi Olagunsoye Oyinlọla ni ọdun 2003.
O kede ipinnu rẹ lati gbe apoti ibo fun gomina ni ọdun 2010 laarin awọn oludije mẹrinla miiran, ṣugbọn ipinnu naa f'ori sanpọn.
Akinbade di oludije ẹgbẹ oṣelu ADC lẹyin ọsẹ meji to fi ẹgbẹ PDP silẹ.
Ademola Adeleke
People's Democratic Party (PDP)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
A bí Ademola Jackson Adeleke Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù karún-un ọdún 1960 ní ìpínlẹ̀ Enugu ní ìdílé sínatọ̀ Raji Ayoola àti Nnena Esther Adeleke ní ìlú Ede
Ó lọ sí iléèwé alákọ̀ọ́bẹ̀rẹ̀ Methodist ní Surulere àti Nuwarudeen ní Ikire, bákan náà ló lọ iléèwé Seventh Day àti iléèwé Muslim Grammar ni ìlú Ede tí ó sì kọ́ ẹ̀kọ́ ìmọ̀ nípa ìwádìí ọ̀daràn ní Jacksonville State University Alabama USA.
Ó jẹ́ adarí àgbà ní iléeṣẹ́ Pacific Holdings Limited láti 2001 sí 2006 àti Quicksilver Courier Company ní Atlanta, Georgia láti 1985 sí 1989
Ademola Adeleke bẹ̀rẹ̀ òṣèlú ní ọdún 2007, ó sì dí sẹ́nétọ̀ tó ń sojú ẹkùn ìwọ̀-oòrùn Oṣun lẹ̀yìn ikú ẹgbọn rẹ̀ sẹ́nétọ̀ Isiaka Adeleke tó jẹ́ Gomìnà alágbádá àkọ́kọ́ ní ìpínlẹ̀ náà
Senator Iyiola Omisore
Social Democratic Party (SDP)
Kíni ọjọ́ ìbí yin?
Iṣẹ́ wo ni ẹ̀ ń ṣe?
Ìkádìí
Wọ́n bí Iyiọla Ajani Omisore sí ìdílé ọba ní ọjọ́ kẹẹ̀dógún, oṣù Kẹsàn án, ọdún 1957 ní ìlú Ilé-Ifẹ̀.
Omisore jẹ igbákejì gómìnà ìpínlẹ̀ Ọṣun, Adebisi Akande láàrin ọdún 1999- 2003.
Wọ́n dìbò yàn án sí ipò sẹ́nétọ̀ láti ṣojú ẹkùn ìdìbò ìlà oòrùn Ọṣun l'ábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú PDP láàrin ọdún 2003 sí 2007, wọ́n tún padà dìbò yàn án ní 2007.
Ó díje fún ipò gómìnà ìpínlẹ̀ Ọṣun l'ọ́dún 2014 l'ábẹ́ àsìá ẹgbẹ́ òṣèlú Peoples Democratic Party, PDP, sùgbọ́n Rauf Aregbẹsọla fi ẹ̀yìn rẹ̀ janlẹ̀ nínú ètò ìdìbò nàá tó wáyé ní ọjọ́ kẹsàn án, oṣù Kẹjọ 2014.